Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 54:6-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Olúwa yóò pè ọ́ padàà fi bí ẹni pé obìnrin tí a kọ̀ sílẹ̀tí a sì bà lọ́kàn jẹ́obìnrin tí a fẹ́ ní ọ̀dọ́,tí a sì wá já kulẹ̀” ni Olúwa wí.

7. “Fún ìgbà díẹ̀ ni mo kọ̀ ọ́ sílẹ̀,ṣùgbọ́n pẹ̀lú ọkàn ìyọ́nú èmi yóòmú ọ padà wá.

8. Ní ríru ìbínú.Mo fi ojú pamọ́ fún ọ fún ìṣẹ́jú kan,ṣùgbọ́n pẹ̀lú àánú àìnípẹ̀kunÈmi yóò síjú àánú wò ọ́,”ni Olúwa Olùdáǹdè rẹ wí.

9. “Sí mi, èyí dàbí i àwọn ọjọ́ Núà,nígbà tí mo búra pé àwọn omiNúà kì yóò tún bo ilẹ̀ ayé mọ́.Bẹ́ẹ̀ ni nísinsìnyìí mo ti búra láti má ṣe bínú sí ọ,bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá ọ wí mọ́.

10. Bí a tilẹ̀ mi àwọn òkè ńlátí a sì sí àwọn òkè kékeré nídìí,Ṣíbẹ̀ ṣíbẹ̀ ìfẹ́ àìkùnà mi fún ọ kì yóò yẹ̀ láéláétàbí májẹ̀mú àlàáfíà ni a ó mú kúrò,”ni Olúwa, ẹni tí ó síjú àánú wò ọ́ wí.

11. Ìwọ ìlú tí a pọ́n lójú, tí ìjì ń gbá kirití a kò sì tù nínú,Èmi yóò fi òkúta tìróò kọ́ ọàti ìpìlẹ̀ rẹ pẹ̀lú sáfírésì.

Ka pipe ipin Àìsáyà 54