Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 54:4-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. “Má ṣe bẹ̀rù, ìtìjú kò ní ṣubú lù ọ́.Má ṣe bẹ̀rù ìdójútì, a kì yóò kàn ọ́ lábùkù.Ìwọ yóò gbàgbé ìtìjú ìgbà èwee rẹÌwọ kì yóò sì rántí ẹ̀gàn ìwà-rópó rẹ mọ́.

5. Nítorí Ẹlẹ́dáà rẹ ni ọkọ rẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì ni Olùràpadà rẹ;a sì pè é ní Ọlọ́run gbogbo ayé.

6. Olúwa yóò pè ọ́ padàà fi bí ẹni pé obìnrin tí a kọ̀ sílẹ̀tí a sì bà lọ́kàn jẹ́obìnrin tí a fẹ́ ní ọ̀dọ́,tí a sì wá já kulẹ̀” ni Olúwa wí.

7. “Fún ìgbà díẹ̀ ni mo kọ̀ ọ́ sílẹ̀,ṣùgbọ́n pẹ̀lú ọkàn ìyọ́nú èmi yóòmú ọ padà wá.

Ka pipe ipin Àìsáyà 54