Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 51:2-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. ẹ wo Ábúráhámù baba yín,àti Ṣérà, ẹni tó bí i yín.Nígbà tí mo pè é, òun nìkan ni,Èmi sì bùkún un, mo sì sọ́ọ́ di ọ̀pọ̀lọpọ̀.

3. Dájúdájú, Olúwa yóò tu Ṣíhónì nínúyóò sì bojú àánú wo gbogbo ahoro rẹ̀;Òun yóò sọ gbogbo aṣálẹ̀ rẹ̀ di Ídẹ́nì,gbogbo ìgbòrò rẹ̀ yóò rí bí ọgbà Olúwa.Ayọ̀ àti inúdídùn ni a ó rí nínú rẹ̀,ọpẹ́ àti ariwo orín kíkọ.

4. “Tẹ́tí sími, ẹ̀yin ènìyàn mi;gbọ́ tèmi, ẹ̀yin orílẹ̀ èdè mi:Òfin yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde wá;ìdájọ́ mi yóò di ìmọ́lẹ̀ sí àwọn orílẹ̀ èdè.

5. Òdodo mi ń bọ̀ wá kíkankíkan,ìgbàlà mi ń bọ̀ lójú ọ̀nà,àti apá mi yóò sì mú ìdájọ́ wásí àwọn orílẹ̀ èdè.Àwọn erékùṣù yóò wò míwọn yóò sì dúró ní ìrètí fún apá mi.

Ka pipe ipin Àìsáyà 51