Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 44:25-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. “ta ni ó ba àmì àwọn wòlíì èké jẹ́tí ó sì sọ àwọn tí ń woṣẹ́ fún ni di òmùgọ̀,tí ó dojú ìmọ̀ àwọn ọlọgbọ́n délẹ̀tí ó sì sọ wọ́n di òmùgọ̀,

26. ẹni tí ó gbé ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ jádetí ó sì mú àṣọtẹ́lẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìmúṣẹ,“ẹni tí ó wí nípa ti Jérúsálẹ́mù pé,‘a ó máa gbénú un rẹ̀,’àti ní ti àwọn ìlú Júdà, ‘A ó tún un kọ́,’àti àwọn ahoro rẹ̀, ‘Èmi yóò mú un bọ̀sípò,’

27. ta ni ó sọ fún omi jínjìn pé, ‘Ìwọ gbẹ,èmi yóò sì mú omi odò rẹ gbẹ,’

28. ta ni ó sọ nípa Ṣáírọ́ọ́ṣì pé, ‘Òun ni Olùṣọ́-àgùntàn miàti pé òun yóò ṣe ohun gbogbo tí mo fẹ́;òun yóò sọ nípa Jérúsálẹ́mù pé, “Jẹ́ kí a tún un kọ́,”àti nípa tẹ́ḿpìlì, “Jẹ́ kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀.” ’

Ka pipe ipin Àìsáyà 44