Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 41:5-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Àwọn erékùsù ti rí i wọ́n bẹ̀rù;ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé wárìrì.Wọ́n súnmọ́tòsí wọ́n sì wá síwájú

6. Èkínní ran èkejì lọ́wọ́ó sì sọ fún arákùnrin rẹ̀ pé“Jẹ́ alágbára!”

7. Oníṣọ̀nà gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjú,àti ẹni tí ó fi òòlù dán anmú òun lọ́kàn le, àní ẹni tí ó ń lu owú.Ó sọ nípa àjópọ̀ náà pé, “Ó dára.”Ó kan ère náà mọ́lẹ̀ kí ó má ba à wó lulẹ̀.

8. “Ṣùgbọ́n ìwọ, Ìwọ Ísírẹ́lì, ìránṣẹ́ mi,Jákọ́bù, ẹni tí mo ti yàn,ẹ̀yin ìran Ábúráhámù, ọ̀rẹ́ mi,

9. mo mú ọ láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé,láti kọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ó jìnnà jùlọ ni mo ti pè ọ́.Èmi wí pé, ‘Ìwọ ni ìránṣẹ́ mi;’Èmi ti yàn ọ́ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì tí ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.

10. Nítorí náà má bẹ̀rù, nítorí èmi wà pẹ̀lúù rẹ;má ṣe jẹ́ kí àyà kí ó fò ọ́, nítorí èmi ni Ọlọ́run rẹ.Èmi yóò fún ọ lókun èmi ó sì ràn ọ́ lọ́wọ́.Èmi ó gbé ọ ró pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi.

11. “Gbogbo àwọn tí ó bínú sí ọni ojú yóò tì, tí wọn yóò sì di ẹni yẹ̀yẹ́;gbogbo àwọn tí ó lòdì sí ọyóò dàbí asán, wọn yóò ṣègbé.

12. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yóò wá àwọn ọ̀ta rẹ,ìwọ kì yóò rí wọn.Gbogbo àwọn tí ó gbógun tì ọ́yóò dàbí òfuuru gbádá.

13. Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,tí ó di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mútí ó sì sọ fún ọ pé, má ṣe bẹ̀rù;Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.

14. Ìwọ má ṣe bẹ̀rù, Ìwọ Jákọ́bù kòkòrò,Ìwọ Ísírẹ́lì kékeré,nítorí Èmi fúnra mi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́,”ni Olúwa wí,olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Ísírẹ́lì.

Ka pipe ipin Àìsáyà 41