Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 35:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Aṣálẹ̀ àti ìyàngbẹ ilẹ̀ ni inú rẹ̀ yóò dùn;ihà yóò ṣe àjọyọ̀ yóò sì kún fún ìtànná.Gẹ́gẹ́ bí ewéko kúrókúsì,

2. òun yóò bẹ́ná jáde;yóò yọ ayọ̀ ńlá ńlá yóò sì kígbe fún ayọ̀.Ògo Lẹ́bánónì ni a ó fi fún un,ọlá ńlá Kámẹ́lì àti Ṣárónì;wọn yóò rí ògo Olúwa,àti ọlá ńlá Ọlọ́run wa.

3. Fún ọwọ́ àìlera lókun,mú orúnkún tí ń yẹ̀ lókun:

4. Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé“Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù;Ọlọ́run yín yóò wá,òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀ṣan;pẹ̀lú ìgbẹ̀ṣan mímọ́òun yóò wá láti gbà yín là.”

5. Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́júàti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.

Ka pipe ipin Àìsáyà 35