Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 32:4-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ọkàn àwọn oníwàdùwàdù ni yóò là tí yóò sì yè,àti ahọ́n tí ń kólòlò ni yóò là geerege.

5. A kò ní pe òmùgọ̀ ní bọ̀rọ̀kìnní mọ́tàbí kí a fi ọ̀wọ̀ tí ó ga jù fún mọ̀dàrú.

6. Nítorí òmùgọ̀ ṣọ̀rọ̀ òmùgọ̀,ọkàn rẹ̀ kún fún ìwà ibi:òun hùwà àìwà-bí-Ọlọ́runó sì ń tan àṣìṣe tí ó kan Olúwa kalẹ̀;ẹni ebi ń pa ló fi sílẹ̀ lófoàti fún àwọn tí òrùngbẹ ń gbẹni ó mú omi kúrò.

7. Ìlànà àwọn aṣa jẹ ti ìkà,ó pète oríṣìí ìlànà ibiláti pa aláìní run pẹ̀lú irọ́bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀bẹ̀ òtòsì sì tọ̀nà.

8. Ṣùgbọ́n bọ̀rọ̀kìnní ènìyàn a máa pète ohun ńláàti nípa èrò rere ni yóò dúró.

9. Ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ti gba ìtẹ́lọ́rùn gidiẹ dìde kí ẹ tẹ́tí sí mi,ẹ̀yin ọ̀dọ́mọbìnrin tí ọkàn yín ti balẹ̀,ẹ gbọ́ ohun tí mo fẹ́ sọ!

10. Ní ó lé díẹ̀ ní ọdún kanẹ̀yin tí ọkàn an yín balẹ̀ yóò wárìrì;ìkóórè àjàrà kò ní múnádóko,bẹ́ẹ̀ ni ìkóórè èṣo kò ní sí.

11. Wárìrì, ẹ̀yin obìnrin onítẹ̀lọ́rùnbẹ̀rù, ẹ̀yin ọ̀dọ́mọbìnrin tí ẹ rò pé ọkàn yín balẹ̀!Ẹ bọ́ aṣọ yín kúrò,ẹ ró aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ẹ yín.

12. Ẹ lu ọmú un yín fún pápá ìgbádùn náà,fún àwọn àjàrà eléso

Ka pipe ipin Àìsáyà 32