Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 3:3-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. balógun àádọ́ta àti bọ̀rọ̀kìnní ènìyàn,olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́àti ògbójú oníṣegùn.

4. Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn,ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sìmáa jọba lóríi wọn.

5. Àwọn ènìyàn yóò sì má a pọ́nọmọnìkejì wọn lójúẹnìkan sí ẹnìkejìi rẹ̀, aládùúgbòsí aládùúgbò rẹ̀.Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbogun ti àwọn àgbà,àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí bọ̀rọ̀kìnní.

6. Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínu àwọnarákùnrin rẹ̀ múnínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé,“Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa,sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”

7. Ṣùgbọn ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé,“Èmi kò ní àtúnṣe kan.Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ò ní aṣọ nílé,ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”

8. Jérúsálẹ́mù ń ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́nJúdà ń ṣubú lọ,ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa,láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.

9. Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn,wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sódómù;wọn ò fi pamọ́!Ègbé ni fún wọn!Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.

10. Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn,nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èṣo iṣẹ́ ẹ wọn.

11. Ẹ̀gbé ni fún aṣebi! Ìparun wà lóríi wọnA ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.

Ka pipe ipin Àìsáyà 3