Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 3:11-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ẹ̀gbé ni fún aṣebi! Ìparun wà lóríi wọnA ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.

12. Àwọn ọ̀dọ̀mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójúàwọn obìnrin ń jọba lé wọn lórí.Áà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti sìyín lọ́nà,wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.

13. Olúwa bọ sí ipo rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.

14. Olúwa dojú ẹjọ́ kọàwọn alàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀.“Ẹyin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi,ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.

15. Kín ni èro yín láti máa run àwọnènìyàn mi túútúútí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ?”ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

16. Olúwa wí pé,“Àwọn obìnrin Ṣíónì jẹ́ agbéraga,wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn,tí wọn ń fojú pe ọkùnrin,tí wọn ń sọ̀dí bí wọn ti ń yan lọpẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjan wọnjan lọ́rùn ẹṣẹ̀ wọn.

Ka pipe ipin Àìsáyà 3