Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 29:8-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá péòun ń jẹun,ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lúu rẹ̀;àti bí ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ lá àlá péòun ń mumi,ṣùgbọ́n nígbà tí ó yajú pẹ́ ẹ́, pẹ̀lú òùngbẹtí kò dáwọ́ dúró ni.Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀ èdètí ń bá òkè Ṣíhónì jà.

9. Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín,ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran;ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì,ẹ ta gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n, ṣùgbọ́n kì í se ti ọtí bíà.

10. Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sóríi yín:ó ti dì yín lójú (ẹ̀yin wòlíì);ó ti bo oríi yín (ẹ̀yin aríran).

11. Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.”

Ka pipe ipin Àìsáyà 29