Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 19:22-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-àrùn kan bá Éjíbítì jà; yóò bá wọn jà yóò sì tún wò wọ́n sàn. Wọn yóò yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn yóò sì wò wọ́n sàn.

23. Ní ọjọ́ náà òpópónà kan yóò wá láti Éjíbítì lọ sí Ásíríà. Àwọn ará Ásíríà yóò lọ sí Éjíbítì àti àwọn ará Éjíbítì lọ sí Ásíríà. Àwọn ará Éjíbítì àti ará Ásíríà yóò jọ́sìn papọ̀.

24. Ní ọjọ́ náà Ísírẹ́lì yóò di ẹ̀kẹta pẹ̀lú Éjíbítì àti Áṣíríà, àní oríṣun ìbùkún ní ilẹ̀ ayé.

25. Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò bùkún wọn yóò wí pé, “Ìbùkún ni fún Éjíbítì ènìyàn mi, Áṣíríà iṣẹ́ ọwọ́ mi, àti Ísírẹ́lì ìní mi.”

Ka pipe ipin Àìsáyà 19