Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 15:2-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Díbónì gòkè lọ sí tẹ́ḿpìlìi rẹ̀,sí àwọn ibi gíga rẹ̀ láti ṣunkún,Móábù pohùnréré lórí Nébónì àti Médíbà.Gbogbo orí ni a fágbogbo irungbọ̀n ni a gé dànù.

3. Wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀ ní ojú òpópónà,ní àwọn òrùlé àti àwọn gbàgede àkójọwọ́n pohùnréré,Wọ́n dọ̀bálẹ̀ pẹ̀lú ẹkún.

4. Hẹ́ṣíbónì àti Élíálè ké ṣóde,ohùn wọn ni a gbọ́ títí fi dé Jáhásì.Nítorí náà ni àwọn ọmọ ogun Móábù ṣe kígbetí ọkàn wọn sì rẹ̀wẹ́sì.

5. Ọkàn mi kígbe lórí Móábù;àwọn ìṣáǹṣá rẹ sálà títí dé Ṣóárì,títí fi dé Égílátì Ṣẹ́líṣíyà.Wọ́n gòkè lọ títí dé Lúhítìwọ́n ń ṣunkún bí wọ́n ti ń lọ,Ní òpópónà tí ó lọ sí Hórónáímùwọ́n ń pohùnréré ìparun wọn

6. Gbogbo omi Nímírímù ni ó ti gbẹàwọn koríko sì ti gbẹ,gbogbo ewéko ti tánewé tútù kankan kò sí mọ́.

7. Báyìí gbogbo ọrọ̀ tí wọ́n ti nítí wọ́n sì tòjọwọ́n ti kó wọn kọjá lọ lóríi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́odò pópúlárì.

Ka pipe ipin Àìsáyà 15