Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 12:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ náà ìwọ ó wí pé:“Èmi ó yìn ọ́, Olúwa.Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ò ti bínú sí miìbínú rẹ ti yí kúrò níbẹ̀ìwọ sì ti tù mí nínú.

2. Nítòótọ́ Ọlọ́run ni ìgbàlà mi,Èmi yóò gbẹ́kẹ̀lé e èmi kì yóò bẹ̀rù. Olúwa, Olúwa náà ni agbára à mi àti orin ìn mi,òun ti di ìgbàlà mi.”

3. Pẹ̀lú ayọ̀ ni ìwọ yóò máa pọn omiláti inú un kànga ìgbàlà.

4. Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò wí pé:“Fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀,Jẹ́ kí ó di mímọ̀ láàrin àwọn orílẹ̀ èdè,ohun tí ó ti ṣekí o sì kéde pé a ti gbéorúkọ rẹ̀ ga.

5. Kọ orin sí Olúwa, nítorí ó ti ṣe ohun tí ó lógo,jẹ́ kí èyí di mímọ̀ fún gbogbo ayé.

Ka pipe ipin Àìsáyà 12