Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 10:19-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Àwọn igi tí yóò kù nínú igbóo rẹ̀yóò kéré níye,tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.

20. Ní ijọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Ísírẹ́lìÀwọn tí ó yè ní ilée Jákọ́bùkò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náàtí ó lùwọ́n bolẹ̀ṣùgbọ́n yóò gbẹ́kẹ̀lé OlúwaẸni Mímọ́ Ísírẹ́lì.

21. Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jákọ́bùyóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.

22. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn an rẹ, ìwọ Ísírẹ́lìdàbí yanrìn ní òkun,ẹni díẹ̀ ni yóò padà.A ti pàṣẹ ìparunà kún wọ́ sílẹ̀ àti òdodo.

23. Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú-un ṣẹ,ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórígbogbo ilẹ̀ náà.

24. Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí,“Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Ṣíhónì,Ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Ásíríà,tí ó ń fi ọ̀pá lù yín,tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tìyín bíÉjíbítì ti ṣe.

25. Láìpẹ́, ìbínú mi síi yín yóò wá sí òpinn ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n,fún ìparun wọn.”

26. Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò nà wọ́n ní ẹgba.Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe lu Mídíánìní òkè Órébù,yóò sì gbé ọ̀páa rẹ̀ lé orí omigẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Éjíbítì.

27. Ní ọjọ́ náà, a ó gbé ẹrùu wọn kúrò ní èjìká a yín,àti àjàgà a wọn kúrò ní ọrùn un yína ó fọ́ àjàgà náà,nítorí pé ẹ̀yin ó ti sanra.

28. Wọ́n wọ Áíyátì,Wọ́n gba Mígírónì kọjáWọ́n kó nǹkan pamọ́ sí Mísímásì.

29. Wọ́n ti rékọjá ọ̀nà, wọ́n wí pé,“Àwa ó tẹ̀dó sí Gébà lóru yìí.”Rámà mì tìtìGíbíà ti Ṣọ́ọ̀lù sá lọ.

30. Kígbe ṣókè, ìwọ ọmọbìnrin GálímùDẹtísílẹ̀, Ìwọ LáíṣàÒpè Ánátótì.

31. Mádíménà ti fẹṣẹ̀ fẹ́ ẹÀwọn ènìyàn Gébímù ti farapamọ́.

32. Ní ọjọ́ yìí, wọn yóò dúró ní Nóbùwọn yóò kan sáárá,ní òkè ọmọbìnrin Ṣíhónìní òkè Jérúsálẹ́mù.

33. Wò ó, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,yóò kán ẹ̀ka náà sọnù pẹ̀lú agbára.Àwọn igi ọlọ́lá ni a ó gé lulẹ̀Àwọn tí ó ga gogoro ni a ó rẹ̀ sílẹ̀.

Ka pipe ipin Àìsáyà 10