Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 1:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ìran sí Júdà àti Jérúsálẹ́mù èyí tí Àìṣáyà ọmọ Ámọ́sì rí ní àsìkò ìjọba Hùṣáyà, Jótamù, Áhásì àti Heṣekáyà àwọn ọba Júdà.

2. Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé!Nítorí Olúwa ti sọrọ̀:“Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà,Ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.

3. Màlúù mọ olówó rẹ̀,kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀,ṣùgbọ́n Ísírẹ́lì kò mọ̀,òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”

4. Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀,àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù,Ìran àwọn aṣebi,àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́!Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀wọn ti gan Ẹni-Mímọ́ Ísírẹ́lì,wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.

Ka pipe ipin Àìsáyà 1