Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 24:7-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Wọ́n sì wá sí ìlú olodi Tírè, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hífì, àti ti àwọn ará Kénánì: wọ́n sì jáde lọ síhà gúsù ti Júdà, àní sí Bééríṣébà.

8. Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jérúsálẹ́mù ní òpin oṣù kẹsàn-án àti ogúnjọ́.

9. Jóábù sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́: ó sì jẹ́ òjì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Ísírẹ́lì, àwọn onídà: àwọn ọkùnrin Júdà sì jẹ́ ọkẹ mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n ènìyàn.

10. Àyà Dáfídì sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dáfídì sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe: ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jìn ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”

11. Dáfídì sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gádì wòlíì wá, aríran Dáfídì wí pé:

12. “Lọ kí o sì wí fún Dáfídì pé, ‘Bàyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’ ”

13. Gádì sì tọ Dáfídì wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀ta rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí àrun ìparun ijọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Ròó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 24