Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 24:5-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Wọ́n sì kọjá odò Jọ́dánì, wọ́n sì pàgọ́ ní Áróérì, ní ìhà apá ọtún ìlú tí ó wà láàrin àfonífojì Gádì, àti sí ìhà Jásérì.

6. Wọ́n sì wá sí Gílíádì, àti sí ilé Tátímhódíṣì; wọ́n sì wá sí Dan-Jaanì àti yíkákiri sí Sídónì,

7. Wọ́n sì wá sí ìlú olodi Tírè, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hífì, àti ti àwọn ará Kénánì: wọ́n sì jáde lọ síhà gúsù ti Júdà, àní sí Bééríṣébà.

8. Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jérúsálẹ́mù ní òpin oṣù kẹsàn-án àti ogúnjọ́.

9. Jóábù sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́: ó sì jẹ́ òjì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Ísírẹ́lì, àwọn onídà: àwọn ọkùnrin Júdà sì jẹ́ ọkẹ mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n ènìyàn.

10. Àyà Dáfídì sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dáfídì sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe: ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jìn ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”

11. Dáfídì sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gádì wòlíì wá, aríran Dáfídì wí pé:

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 24