12. “Lọ kí o sì wí fún Dáfídì pé, ‘Bàyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’ ”
13. Gádì sì tọ Dáfídì wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀ta rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí àrun ìparun ijọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Ròó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
14. Dáfídì sì wí fún Gádì pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí a fi ara wa lé Olúwa lọ́wọ́; nítorí pé àánú rẹ̀ pọ̀; kí ó má sì ṣe fi mí lé ènìyàn lọ́wọ́.”
15. Olúwa sì rán àrùn ìparun sí Ísírẹ́lì láti òwúrọ̀ títí dé àkókò tí a dá: ẹgbàá márùndínlógójì ènìyàn sì kú nínú àwọn ènìyàn náà láti Dánì títí fi dé Bééríṣébà.