Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 15:8-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ti jẹ́jẹ̀ẹ́ kan nígbà tí èmi ń bẹ ní Géṣúrì ní Síríà pé, ‘Bí Olúwa bá mú mi padà wá sí Jérúsálẹ́mù, nítòótọ́, èmi ó sì sin Olúwa.’ ”

9. Ọba sì wí fún un pé, “Má a lọ ní àlàáfíà.” Ó sì dìde, ó sì lọ sí Hébúrónì.

10. Ṣùgbọ́n Ábúsálómù rán àmì sáàrin gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá gbọ́ ìró ìpè, kí ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ábúsálómù jọba ní Hébúrónì.’ ”

11. Igba ọkùnrin sì bá Ábúsálómù ti Jérúsálẹ́mù jáde, nínú àwọn tí a ti pè; wọ́n sì lọ nínú àìmọ̀kan wọn, wọn kò sì mọ nǹkankan.

12. Ábúsálómù sì ránṣẹ́ pe Áhítófélì ará Gílónì, ìgbìmọ̀ Dáfídì, láti ìlú rẹ̀ wá, àní láti Gílónì, nígbà tí ó ń rú ẹbọ. Ìdìmọ̀lù náà sì le; àwọn ènìyàn sì ń pọ̀ sọ́dọ̀ Ábúsálómù.

13. Ẹnìkan sì wá rò fún Dáfídì pé, “Ọkàn àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì ṣí sí Ábúsálómù.”

14. Dáfídì sì wí fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wá lọ́dọ̀ rẹ̀ ni Jérúsálẹ́mù pé, “Ẹ dìde! Ẹ jẹ́ kí a sá lọ, nítorí pé kò sí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ Ábúsálómù; ẹ yára, kí a lọ kúrò, kí òun má báà yára lé wa bá, kí ó má sì mú ibi bá wa, kí ó má sì fi ojú idà pa ìlú run.”

15. Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa wa ọba ń fẹ́, wò ó, àwa ìránṣẹ rẹ̀ ti murá.”

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 15