Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 10:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Nígbà tí Jóábù sì ríi pé ogun náà dojú kọ òun níwájú àti lẹ́yìn, ó sì yàn nínú gbogbo àwọn akíkanjú ọkùnrin ní Ísírẹ́lì, ó sì tẹ́ ogun kọjú sí àwọn ará Síríà.

10. Ó sì fi àwọn ènìyàn tí ó kù lé Ábíṣáì àbúrò rẹ̀ lọ́wọ́, kí ó lè tẹ ogun kọjú sí àwọn ọmọ Ámónì.

11. Ó sì wí pé, “Bí agbára àwọn ará Síríà bá pọ̀ ju èmi lọ, ìwọ yóò sì wá ràn mí lọ́wọ́: ṣùgbọ́n bí ọwọ́ àwọn ọmọ Ámónì bá sì pọ̀ jù ọ́ lọ, èmi ó sì wá ràn ọ́ lọ́wọ́.

12. Mú ọkàn lè, jẹ́ kí a ṣe onígboyà nítorí àwọn ènìyàn wa, àti nítorí àwọn ìlú Ọlọ́run wa; Olúwa yóò sì ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ̀.”

13. Jóábù àti àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì bá àwọn ará Síríà pàdé ìjà: wọ́n sì sá níwájú rẹ̀.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 10