Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 10:13-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Jóábù àti àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì bá àwọn ará Síríà pàdé ìjà: wọ́n sì sá níwájú rẹ̀.

14. Nígbà tí àwọn ọmọ Ámónì sì ríi pé àwọn ará Síríà sá, àwọn pẹ̀lú sì sá níwájú Ábíṣáì, wọ́n sì wọ inú ìlú lọ. Jóábù sì padà kúrò lẹ́yìn àwọn ọmọ Ámónì, ó sì wá sí Jérúsálẹ́mù.

15. Nígbà tí àwọn ará Síríà sì ríi pé Àwọn ṣubú níwájú Ísírẹ́lì: wọ́n sì kó ara wọn jọ

16. Hadadésérì sì ránṣẹ́, ó sì mú àwọn Síríà tí ó wà ní òkè odò jáde wá: wọ́n sì wá sí Hélámì; Sóbákì olórí ogun Hedareṣérì sì ṣe olórí wọn.

17. Nígbà tí a sọ fún Dáfídì, ó sì kó gbogbo Ísírẹ́lì jọ, wọ́n sì kọjá Jọ́dánì, wọ́n sì wá sí Hélámì, Àwọn ará Síríà sì tẹ́ ogun kọjú sí Dáfídì, wọ́n sì bá a jà.

18. Àwọn ará Síríà sì sá níwájú Ísírẹ́lì, Dáfídì sì pa nínú àwọn ará Síríà ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àwọn oníkẹ̀kẹ́, àti ọ̀kẹ́ méjì ẹlẹ́ṣin, wọ́n sì kọlu Sóbákì olórí ogun wọn, ó sì kú níbẹ́.

19. Nígbà tí gbogbo àwọn ọba tí ó wà lábẹ́ Hadadésérì sì ríi pé wọ́n di bíbì ṣubú níwájú Ísírẹ́lì, wọ́n sì bá Ísírẹ́lì làjà, wọ́n sì ń sìn wọ́n.Àwọn ará Síríà sì bẹ̀rù lati máa ran àwọn ọmọ Ámónì lọ́wọ́ mọ́.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 10