Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 10:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, ọba àwọn ọmọ Ámónì sì kú, Hánúnì ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

2. Dáfídì sì wí pé, “Èmi yóò ṣe ooré fún Hánúnì ọmọ Náhásì gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ sì ti ṣe oore fún mi.” Dáfídì sì ìránṣẹ́ láti tù ú nínú láti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wá, nítorí ti baba rẹ̀.Àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì sì wá sí ilé àwọn ọmọ Ámónì.

3. Àwọn olórí àwọn ọmọ Ámónì sì wí fún Hánúnì Olúwa wọn pé, “Ǹjẹ́ o rò pé Dáfídì ń bu ọlá fún baba rẹ nígbà tí ó rán ènìyàn wá láti bá ọ kẹ́dùn? Kò ha ṣe pé Dáfídì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ọ láti wo ìlú àti láti yọ́ ọ wò àti láti gbà ọ́.”

4. Hánúnì sì mú àwọn ìránṣẹ Dáfídì ó fá apákan irungbọ̀n wọn, ó sì gé ààbọ̀ kúró ní agbádá wọn, títí ó fí dé ìdí wọn, ó sì rán wọn lọ.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 10