Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 1:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn ikú Ṣọ́ọ̀lù, Dáfídì ti ibi tí ó ti ṣẹ́gun àwọn ará Ámálékì bọ̀, ó sì dúró ní Síkílágì ní ọjọ́ méjì.

2. Ní ọjọ́ kẹta, ọkùnrin kan dé láti ibi ibùdó Ṣọ́ọ̀lù, pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ tí ó ti ya; àti erùpẹ̀ ní orí rẹ̀. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ Dáfídì, ó wólẹ̀ fún un láti bu ọlá fún un.

3. Dáfídì sì béèrè pé, “Ibo ni ìwọ ti wá?”“Èmi sá láti ibùdó àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.”

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 1