Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 6:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Èlíṣà pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.

2. Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jọ́dánì, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.”Ó sì wí pé, “lọ.”

3. Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Ṣé ìwọ kò ní jọ̀wọ́ wa pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ?”“Èmi yóò lọ,” Èlíṣà dá a lóhùn.

4. Ó sì lọ pẹ̀lú wọn.Wọ́n sì lọ sí Jọ́dánì wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi

5. Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kí gbe sókè pé, o! Olúwa mi, “mo yá a ni”

6. Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Èlíṣà ge igi kan ó sì jù ú síbẹ́, ó sì mú irin náà fò lójú omi.

7. Ó wí pé, “Gbé e jáde” Nígbà náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.

8. Nísinsìn yìí ọba Árámù ó wà ní ogun pẹ̀lú Ísírẹ́lì ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbérò, ó wí pé “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”

9. Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Ísírẹ́lì, “kíyèsí ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Árámù wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”

10. Bẹ́ẹ̀ ni ọba Ísírẹ́lì wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fi hàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Èlíṣà kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.

11. Èyí mú ọba Árámù bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún un èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Ísírẹ́lì?”

12. “Kò sí ọ̀kan nínú wa, Olúwa ọba mi,” ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “ṣùgbọ́n Èlíṣà, wòlíì tí ó wà ní Ísírẹ́lì, sọ fún ọba Ísírẹ́lì ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.

Ka pipe ipin 2 Ọba 6