Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 25:9-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. ó sì finá sí ilé Olúwa, ilé ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà ní Jérúsálẹ́mù àti gbogbo ilé pàtàkì, ó jó wọn níná.

10. Gbogbo àwọn ọmọ ogun Bábílónì, lábẹ́ olórí ti ìjọba ẹ̀sọ́, wó ògiri tí ó yí Jérúsálẹ́mù ká lulẹ̀.

11. Nebukadinésárí olórí ẹ̀ṣọ́ Kó lọ sí ìgbékùn gbogbo ènìyàn tí ó kù ní ìlú, àti àwọn Ísánsà àti àwọn tí ó ti lo sí ọ̀dọ̀ ọba Bábílón.

12. Ṣùgbọ́n olórí ẹ̀sọ́ fí àwọn talákà ènìyàn ilẹ̀ náà sílẹ̀ láti ṣiṣẹ́ nínú ọgbà àti orí pápá.

13. Àwọn ará Bábílónì fọ́ ọwọ́n idẹ sí túútúú, àti ìjòkòó àti agbada ńlá idẹ tí ó wà nílé Olúwa wọ́n sì kọ́ idẹ wọn sí Bábílónì.

14. Wọ́n sì kóo lọ pẹ̀lú àwo ìkòkò ọkọ́, àlùmágàjí fìtílà, síbí àti gbogbo ohun èló idẹ tí wọ́n lò nílé tí wọ́n fi sisẹ́.

15. Olórí ìjọ̀ba ẹ̀sọ́ mu ìfọnná, àti ọpọ́n, èyí tí wọ́n fi wúrà àti Sílifà ṣe lọ.

16. Bàbà méjì láti ara ọ̀wọ̀n òkú àti ìjòkòó, tí Ṣólómónì ti ṣe fún ilé Olúwa, ó ju èyí tí a lé wọ́n lọ.

17. Ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀wọ̀n gíga rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ ẹsẹ̀ méjìlélógún Olórí Bàbà lórí ọkẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀wọ̀n ọ̀gá ni ìwọ̀n mẹ́rin àti ààbò wọn sì ṣe lọ́sọ́ọ̀ pẹ̀lú iṣe àwọ̀n àti àwọ pòmégránátè tí ó wà lórí ọ̀nà orí gbogbo rẹ̀ yíká, ọ̀wọ̀n mìíràn, pẹ̀lú iṣẹ́ híhun, wọ́n sì kéré.

18. Olórí àwọn ọ̀sọ́ sì mú gẹ́gẹ́ bí olórí àwọn ẹlẹ́wọ̀n Ṣéráíáyà olórí àwọn àlùfáà, Ṣéfáníà àlùfáà ẹni tí ó kù nínú oyè gíga àti àwọn olùṣọ́nà mẹ́ta.

19. Àti àwọn tí ó kù ní ìlú, ó mú ìjòyè tí ó fi sí ipò olórí àwọn ológun ọkùnrin àti àwọn agbà oní ní ìmọ̀ràn ọba. Ó sì tún mú akọ̀wé tí ó jẹ́ ìjòyè tí ń to àwọn ènìyàn ilé náà àti mẹ́fà nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ tí wọ́n rí ní ìlú.

Ka pipe ipin 2 Ọba 25