Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 20:14-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Nígbà náà Àìṣáyà wòlíì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Heṣekáyà ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ọkùnrin náà sọ, àti níbo ni wọ́n ti ń bọ̀ wá?”“Lati ìlú jínjìn réré,” Hesekíáyà dáhùn. “Wọ́n wá láti Bábílónì.”

15. Wòlíì náà béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí ní ààfin rẹ?”“Wọ́n rí gbogbo nǹkan ní ààfin mi,” Heṣekáyà wí pé. “Kò sí nǹkankan lára àwọn ìṣúra tí èmi kò fi hàn wọ́n.”

16. Nígbà náà Àìsáyà wí fún Heṣekáyà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa:

17. Àkókò náà yóò sì dé nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà ní ààfin àti gbogbo ohun tí baba rẹ̀ ti kó pamọ́ sókè títí di ọjọ́ Òní, wọn yí ó gbe lọ sí Bábílónì, kò sí ohun tí yóò kù, ni Olúwa wí.

Ka pipe ipin 2 Ọba 20