Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 2:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí Ọlọ́run ń fẹ́ gbé Èlíjà lọ sí òkè ọ̀run nínú àjà, Èlíjà àti Èlíṣà wà ní ọ̀nà láti Gílgálì.

2. Èlíjà wí fún Èlíṣà pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Bétélì.”Ṣùgbọ́n Èlíṣà wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa wà láyé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, Èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Bétélì.

3. Àwọn ọmọ wòlíì ní Bétélì jáde wá sí ọ̀dọ̀ Èlíṣà wọ́n sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?”“Bẹ́ẹ̀ ni, Èmi mọ̀,” Èlíṣà dáhùn “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.”

4. Nígbà náà Èlíjà sì wí fún un pé, “Dúró níbí, Èlíṣà: Olúwa ti rán mi lọ sí Jẹ́ríkò.”Ó sì dá a lóhùn pé, “Bí ó ti dájú pé Olúwa yè àti tí ìwọ náà yè, Èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Wọ́n sì jọ lọ sí Jẹ́ríkò.

Ka pipe ipin 2 Ọba 2