Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 17:11-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ní gbogbo ibi gíga, wọ́n ṣun tùràrí gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú wọn. Wọ́n ṣe ohun búrubú tí ó rú ìbínú Olúwa sókè.

12. Wọ́n sìn òrìsà, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí.”

13. Olúwa kìlọ̀ fún Ísírẹ́lì àti Júdà nípa gbogbo àwọn wòlíì wọn àti aríran: “Ẹ yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú yín. Kí ẹ ṣe òfin mi àti ìlànà mi, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin tí Èmi palaṣẹ fún àwọn baba yín láti tẹ̀lé àti èyí tí mo rán síi yín nípa ìránṣẹ́ àwọn wòlíì mi.”

14. Ṣùgbọ́n wọn kò ní gbọ́, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́rùn lile gẹ́gẹ́ bí i ti baba wọn, ẹni tí kò gbà Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́.

15. Wọ́n kọ̀ ìlànà rẹ̀ àti májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú baba wọn àti ìkìlọ̀ tí ó ti fi fún wọn. Wọ́n tẹ̀lé òrìṣà aláìníláárí, àwọn fún rara wọn sì jẹ́ aláìníláárí. Wọ́n tẹ̀lé orílẹ̀ èdè tí ó yí wọn ká bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti kìlọ̀ fún wọn pé, “Má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí wọn tí ń ṣe,” wọ́n sì ṣe ohun tí Olúwa ti kà léèwọ̀ fún wọn láti ṣe.

16. Wọ́n kọ̀ gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀ wọ́n sì ṣe òrìṣà méjì fún ara wọn, wọ́n sì gbée sí ọkàn ẹ̀gbọ̀rọ̀ màlúù, àti ère òrìṣà sí ọkàn. Wọ́n sì tẹrí wọn ba sí gbogbo ogun ọ̀run, wọ́n sì sin Báálì.

17. Wọ́n sì fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn rúbọ nínú iná. Wọ́n sì n fọ̀ àfọ̀sẹ, wọ́n sì ń ṣe àlùpàyídà wọ́n sì ta ara wọn láti ṣe ohun búburú níwájú Olúwa, wọ́n sì mú-un bínú.

18. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gídígídí pẹ̀lú Ísírẹ́lì ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Èyà Júdà nìkan ṣoṣo ni ó kù,

19. Àti pẹ̀lú, Júdà kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Ísírẹ́lì tí wọ́n ṣe.

20. Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì; ó sì jẹ wọ́n níyà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè tí tí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.

21. Nígbà tí ó ta Ísírẹ́lì kúrò láti ìdílé Dáfídì, wọ́n sì mú Jéróbámù ọmọ Nébátì jẹ ọba wọn. Jéróbóámù sì mú kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì yípadà kúrò ní tí tẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́sẹ̀ ńlá.

Ka pipe ipin 2 Ọba 17