Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 13:11-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, kò sì yípadà kúrò nínú ọ̀kankan nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jéróbóámù ọmọ Nébátì èyí tí ó ti ti Ísírẹ́lì láti fà. Ó sì tẹ̀síwájú nínú wọn.

12. Fún ti ìyókù iṣẹ́ Jéhóásì fún ìgbà tí ó fi jọba, gbogbo ohun tí ó ṣe, pẹ̀lú àṣeyọrí rẹ̀ pẹ̀lú ogun rẹ̀ sí Ámásáyà ọba Júdà, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Ísírẹ́lì?

13. Jéhóásì sinmi pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀. Jéróbóámù sì rọ́pò rẹ̀ lórí ìtẹ́. A sin Jéhóásì sí Samáríà pẹ̀lú àwọn ọba Ísírẹ́lì.

14. Nísinsìn yìí, Èlíṣà ń jìyà lọ́wọ́ àìsàn, lọ́wọ́ èyí tí ó sì kú. Jéhóásì ọba Ísírẹ́lì lọ láti lọ wò ó, ó sì ṣunkún lórí rẹ̀. “Baba mi!, Baba mi!” Ó ṣunkún. “Àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ọkùnrin ẹlẹ́ṣin Ísírẹ́lì.!”

Ka pipe ipin 2 Ọba 13