Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 6:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà ni Sólómonì wí pé, “Olúwa ti sọ wí pé òun yóò máa gbé nínú ìkùku tí ó ṣú biribiri;

2. ṣùgbọ́n èmi ti kọ́ tẹ́ḿpìlì dáradára fún ọ ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láé.”

3. Ní ìgbà tí gbogbo ìjọ Ísírẹ́lì dúró níbẹ̀, ọba yíjú padà ó sì fi ìbùkún fún gbogbo wọn.

4. Nígbà náà ni ó sì wí pé:“Ògo ni fún Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ mú ohun tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dáfídì baba mi ṣẹ. Nitorí tí ó wí pé,

5. ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì, èmi kò yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì, láti kọ́ ilé, kí orúkọ mi kí ó lè wà níbẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yan ẹnikẹ́ni láti jẹ́ olórí lórí Ísirẹ́lì ènìyàn mi.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 6