Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 4:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ọkùnrin tí ó mú ìròyìn náà wá dáhùn pé, “Ísírẹ́lì sá níwájú àwọn Fílístínì, àwọn ọmọ ogun náà sì kú lọ́pọ̀lọpọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ méjèèjì, Hófínì àti Fínéhásì, wọ́n kú, wọ́n sì ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ”

18. Nígbà tí ó dárúkọ àpótí ẹ̀rí Olúwa, Élì sì ṣubú sẹ́yìn kúrò lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ bodè, ọrùn rẹ̀ ṣẹ́, ó sì kú, nítorí tí ó jẹ́ arúgbó ọkùnrin, ó sì tóbi, ó ti darí àwọn Ísírẹ́lì fún ogójì ọdún.

19. Aya ọmọ rẹ̀, ìyàwó Fínéhásì, ó lóyún ó súnmọ́ àkókò àti bí. Nígbà tí ó gbọ́ ìròyìn náà wí pé wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ àti wí pé baba ọkọ rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀ ti kú, ó rọbí ó sì bímọ, ó sì borí ìrora ìrọbí náà.

20. Bí ó ti ń kú lọ, obìnrin tí ó dúró tì í wí pé, “má ṣe bẹ̀rù; nítorí o ti bí ọmọ ọkùnrin.” Ṣùgbọ́n kò sọ̀rọ̀ tàbí kọ ibi ara sí i.

21. Ó sì pe ọmọ náà ní Íkábódù, wí pé, “Kò sí ògo fún Ísírẹ́lì mọ́” nítorí tí wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àti ikú baba ọkọ rẹ̀ àti ti ọkọ rẹ̀.

22. Ó si wí pé, “Ogo kò sí fún Isirẹli mọ́, nítorí ti a ti gbá àpótí Ọlọ́run”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 4