Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 4:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọ̀rọ̀ Sámúẹ́lì tọ gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wá.Nísinsìnyìí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jáde láti lọ bá àwọn Fílístínì jà. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì pàgọ́ sí Ebenésérì àti àwọn Fílístínì ní Áfékì.

2. Àwọn Fílístínì mú ogun wọn sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Ísírẹ́lì, nígbà tí ogun náà bẹ̀rẹ̀, àwọn Fílístínì ṣẹ́gun Ísírẹ́lì wọ́n pa ẹgbàájì ọkùnrin nínú ogun náà (4,000).

3. Nígbà tí àwọn ọmọ ogun náà padà sí ibùdó, àwọn àgbà Ísírẹ́lì sì béèrè pé, “Èéṣe ti Olúwa fi mú kí àwọn Fílístínì ṣẹ́gun wa lónìí? Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa láti Ṣílò wá, kí ó ba à le lọ pẹ̀lú wa kí ó sì gbàwá là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀ta wa.”

4. Nítorí náà a rán àwọn ènìyàn lọ sí Ṣílò, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àwọn ọmọ ogun wá, ẹni tí ń wà láàrin àwọn Kérúbù àti àwọn ọmọ Élì méjèèjì Hófínì àti Fínéhásì wà níbẹ̀ pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.

5. Nígbà tí àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú Olúwa wá sí ibùdó, gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì dìde láti kígbe tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ sì mì tìtì.

6. Ní ìgbà tí àwọn Fílístínì gbọ́ ariwo náà wọ́n béèrè pé, “Kí ni gbogbo ariwo yìí ní ibùdó Hébérù?”Nígbà tí wọ́n mọ̀ wí pé àpótí ẹ̀rí Olúwa ti wá sí ibùdó,

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 4