Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 3:4-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Nígbà náà ni Olúwa pe Sámúẹ́lì.Sámúẹ́lì sì dáhùn “Èmi nìyí”

5. Ó sì sáré lọ sí ọ̀dọ̀ Élì ó sì wí pé, “Èmi nìyí nítorí pé ìwọ pè mí.”Ṣùgbọ́n Élì wí fún-un pé, “Èmi kò pè ọ́; padà lọ dùbúlẹ̀.” Nítorí náà ó lọ ó sì lọ dùbúlẹ̀.

6. Olúwa sì tún pè é, “Sámúẹ́lì!” Sámúẹ́lì tún dìde ó tọ Élì lọ, ó sì wí pé, “Èmi nì yí, nítorí tí ìwọ pè mí.”“Ọmọ mi, èmi kò pè ọ́, padà lọ dùbúlẹ̀.”

7. Ní àkókò yìí Sámúẹ́lì kò tíì mọ̀ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni a kò sì tí ì fi ọ̀rọ̀ Olúwa hàn án.

8. Olúwa pe Sámúẹ́lì ní ìgbà kẹ́tà, Sámúẹ́lì sì tún dìde, ó sì lọ sọ́dọ̀ Élì ó sì wí pé, “Èmi nì yí; nítorí tí ìwọ pè mí.”Nígbà náà ni Élì wá mọ̀ pé Olúwa ni ó ń pe ọmọ náà.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 3