Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 20:40-42 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

40. Jónátanì sì fí apó àti ọrun rẹ̀ fún ọmọdékùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Lọ, kí o sì mú wọn lọ sí ìlú Para.”

41. Bí ọmọdékùnrin náà ti lọ tán, Dáfídì sì dìde láti ibi òkúta náà, ó sì wólẹ̀, ó sì tẹríba ní ìdojúbolẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹ́ta fún Jónátanì: wọ́n sì fi ẹnu ko ara wọn lẹ́nu, wọ́n sì jùmọ̀ sunkún, èkín-ín-ní pẹ̀lú ikejì rẹ̀, ṣùgbọ́n áfídì sunkún púpọ̀ jù.

42. Jónátanì sì wí fún Dáfídì pé, “Má a lọ ní àlàáfíà, bí o ti jẹ́ pé àwa méjèèjì tí júmọ búra ni orukọ Olúwa pé, ‘Ki Olúwa ó wà láàrin èmi àti ìwọ, láàrin irú-ọmọ mi àti láàrin irú-ọmọ rẹ̀ láéláé.’ ” Òun sì dìde, ó sì lọ kúrò: Jónátanì sì lọ sí ìlú.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 20