Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 8:2-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Gbogbo àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Sólómónì ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Étanímù tí íṣe osù kéje.

3. Nígbà tí gbogbo àwọn àgbà Ísírẹ́lì dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí-ẹ̀rí,

4. wọ́n sì gbé àpótí-ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Léfì sì gbé wọn gòkè wá,

5. Àti Sólómónì ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí-ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rúbọ.

6. Àwọn àlùfáà sì gbé àpótí-ẹ̀rí májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀ sínú ibi tí a yà sí mímọ́, ibi mímọ́ ilé náà, jùlọ lábẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.

7. Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí-ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí-ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.

8. Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti ibi mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde ibi mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.

9. Kò sí ohun kankan nínú àpótí-ẹ̀rí bí kò ṣe tábìlì òkúta méjì tí Mósè ti fi sí ibẹ̀ ní Hórébù, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì.

10. Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti ibi mímọ́, àwọ̀sánmà sì kún ilé Olúwa.

11. Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọ̀sánmà náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.

12. Nígbà náà ni Sólómónì sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri;

Ka pipe ipin 1 Ọba 8