Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 7:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Sólómónì ọba ránṣẹ́ sí Tírè, ó sì mú Hírámù wá,

14. ẹni tí ìyá rẹ̀ jẹ́ opó láti inú ẹ̀yà Náfítalì àti tí baba rẹ̀ sì ṣe ará Tírè, alágbẹ̀dẹ idẹ. Hírámù sì kún fún ọgbọ́n àti òye, àti ìmọ̀ láti ṣe oríṣiríṣi iṣẹ́ idẹ. Ó wá sọ́dọ̀ Sólómónì ọba, ó sì ṣe gbogbo iṣẹ́ tí wọ́n gbé fún un.

15. Ó sì dá ọ̀wọ̀n idẹ méjì, ọ̀kọ̀ọ̀kan sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjìdínlógún ní gíga okùn ìgbọ̀nwọ́ méjìlá ni ó sì yí wọn ká.

16. Ó sì tún ṣe ìparí méjì ti idẹ dídá láti fi sókè àwọn ọ̀wọ̀n náà, ìparí kan sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn ún ní gíga.

17. Onírúurú iṣẹ́, àti ohun híhun ẹ̀wọ̀n fún àwọn ìparí tí ń bẹ lórí àwọn ọ̀wọ̀n náà, méje fún ìparí kọ̀ọ̀kan.

18. Ó sì ṣe àwọn Pómégíránátè ní ọ̀wọ́ méjì yíkákiri lára iṣẹ́ ọ̀wọ̀n náà, láti fi bo àwọn ìparí ti ń bẹ lókè, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀ fún ìparí kejì.

Ka pipe ipin 1 Ọba 7