Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 6:9-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ́ ilé náà, ó sì parí rẹ̀, ó sì bo ilé náà pẹ̀lú àwọn ìtí igi àti pákó Kédárì.

10. Ó sì kọ́ yàrá ẹ̀gbẹ́ sí gbogbo ilé náà. Gígùn ìkọ̀ọ̀kan sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn ún, ó sì so wọ́n mọ́ ilé náà pẹ̀lú ìtì igi Kédárì.

11. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Sólómónì wá wí pé:

12. “Níti ilé yìí tí ìwọ ń kọ́ lọ́wọ́, bí ìwọ bá tẹ̀lé àṣẹ mi, tí ìwọ sì ṣe ìdájọ́ mi, tí o sì pa òfin mi mọ́ láti máa ṣe wọ́n, Èmi yóò mú ìlérí tí mo ti ṣe fún Dáfídì baba rẹ̀ ṣẹ nípa rẹ̀.

13. Èmi yóò sì máa gbé àárin àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, èmi kì ó sì kọ Ísírẹ́lì ènìyàn mi.”

14. Bẹ́ẹ̀ ni Sólómónì kọ́ ilé náà, ó sì parí rẹ̀.

15. Ó sì fi pákó Kédárì tẹ́ ògiri ilé náà nínú, láti ilẹ̀ ilé náà dé àjà rẹ̀, ó fi igi bò wọ́n nínú, ó sì fi pákó fírì tẹ́ ilẹ̀ ilé náà.

16. Ó pín ogún ìgbọ̀nwọ́ sí ẹ̀yìn ilé náà, láti ilẹ̀ dé àjà ilé ni ó fi pákó kọ́, èyí ni ó kọ sínú, fún ibi tí a yà sí mímọ́ àní ibi mímọ́ jùlọ.

17. Ní iwájú ilé náà, ogójì (40) ìgbọ̀nwọ́ ni gígùn rẹ̀ jẹ́.

Ka pipe ipin 1 Ọba 6