Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 3:23-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láàyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láàyè.’ ”

24. Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.

25. Ọba sì pàṣẹ pé: “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”

26. Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láàyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, Olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!”Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ̀. Ẹ gé e sí méjì!”

Ka pipe ipin 1 Ọba 3