Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 22:49-53 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

49. Ní ìgbà náà Áhásáyà ọmọ Áhábù wí fún Jáhósáfátì pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jèhósáfátì kọ̀.

50. Nígbà náà ni Jèhósáfátì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dáfídì, baba rẹ. Jéhórámù ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

51. Áhásáyà ọmọ Áhábù bẹ̀rẹ̀ sí jọba lórí Ísírẹ́lì ní Samáríà ní ọdún kẹtàdínlógún Jèhósáfátì ọba Júdà, ó sì jọba ní ọdún méjì lórí Ísírẹ́lì.

52. Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, nítorí tí ó rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀, àti ní ọ̀nà ìyá rẹ̀, àti ní ọ̀nà Jéróbóámù ọmọ Nébátì, tí ó mú Ísírẹ́lì dẹ́ṣẹ̀.

53. Ó sì sin Báálì, ó sì ń bọ Báálì, ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì bínú, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ ti ṣe.

Ka pipe ipin 1 Ọba 22