Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 22:45-50 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

45. Níti ìyókù ìṣe Jèhósáfátì àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Júdà?

46. Ó pa ìyókù àwọn tí ń hùwà panṣágà ní ọjọ́ Áṣà bàbá rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà.

47. Nígbà náà kò sí ọba ní Édómù; adelé kan ni ọba.

48. Jèhósáfátì kan ọkọ̀ Táríṣíṣì láti lọ sí Ófírì fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ: nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Ésíónì-Gébérì.

49. Ní ìgbà náà Áhásáyà ọmọ Áhábù wí fún Jáhósáfátì pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jèhósáfátì kọ̀.

50. Nígbà náà ni Jèhósáfátì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dáfídì, baba rẹ. Jéhórámù ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Ọba 22