Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 22:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Fún ọdún mẹ́ta kò sì sí ogun láàrin Árámù àti Ísírẹ́lì.

2. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹ́ta, Jèhósáfátì ọba Júdà sọ̀kalẹ̀ lọ láti rí ọba Ísírẹ́lì.

3. Ọba Ísírẹ́lì sì ti wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ti wa ni Ramoti Gílíádì, àwa sì dákẹ́ síbẹ̀, a kò sì gbà á padà lọ́wọ́ ọba Árámù?”

4. Ó sì béèrè lọ́wọ́ Jèhósáfátì pé, “Ṣé ìwọ yóò bá mi lọ láti lọ bá Ramoti-Gílíádì jà?”Jèhóṣáfátì sì dá ọba Ísírẹ́lì lóhùn pé, “Èmi bí ìwọ, ènìyàn mi bí ènìyàn rẹ, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”

5. Ṣùgbọ́n Jèhósáfátì sì tún wí fún ọba Ísírẹ́lì pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”

Ka pipe ipin 1 Ọba 22