Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 21:12-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Wọ́n sì kéde ààwẹ̀, wọ́n sì fi Nábótì sí ipò ọlá láàrin àwọn ènìyàn.

13. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó ṣíwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí pa Nábótì níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Nábótì ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.

14. Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jésébélì wí pé: “A ti sọ Nábótì ní òkúta, ó sì kú.”

15. Bí Jésébélì sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Nábótì ní Òkúta pa, ó sì wí fún Áhábù pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Nábótì, ará Jésérẹ́lì, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láàyè mọ́, ó ti kú.”

16. Nígbà tí Áhábù sì gbọ́ pé Nábótì ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Nábótì.

17. Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Èlíjà ará Tíṣíbì wá wí pé;

18. “Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Áhábù ọba Ísírẹ́lì, tí ó wà ní Samáríà. Ó wà ní ọgbà àjàrà Nábótì báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Ọba 21