Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 2:6-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ṣe sí í gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà-òkú ní àlàáfíà.

7. “Ṣùgbọ́n fi inú rere hàn sí àwọn ọmọ Bárísíláì, ti Gílíádì, jẹ́ kí wọn wà lára àwọn tí ó ń jẹun lórí tábìlì rẹ̀. Wọ́n dúró tì mí nígbà tí mo sá kúrò níwájú Ábúsálómù arákùnrin rẹ̀.

8. “Àti kí o rántí, Ṣíméhì ọmọ Gérà ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì tí Báhúrímù wà pẹ̀lú rẹ̀, tí ó bú mi ní èébú tí ó korò ní ọjọ́ tí mo lọ sí Máhánáímù. Nígbà tí ó sọ̀kalẹ̀ wá pàdé mi ní Jọ́dánì, mo fi Olúwa búra fún un pé: ‘Èmi kì yóò fi idà pa ọ́.’

9. Ṣùgbọ́n nísinsìn yìí, má ṣe kíyèsí í gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin ọlọ́gbọ́n ni ìwọ ṣe; ìwọ yóò mọ ohun tí ìwọ yóò ṣe sí i. Mú ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sínú isà-òkú pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀.”

10. Nígbà náà ni Dáfídì sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dáfídì.

11. Ó ti jọba lórí Ísírẹ́lì ní ogójì ọdún (40): ọdún méje (7) ni Hébúrónì àti ọdún mẹ́talélọ́gbọ̀n (33) ní Jérúsálẹ́mù.

12. Bẹ́ẹ̀ ni Sólómónì jókòó lórí ìtẹ́ Dáfídì baba rẹ̀, ìjọba rẹ̀ sì fi ìdí múlẹ̀ gidigidi.

13. Wàyìí, Àdóníjà ọmọ Hágítì tọ Bátíṣébà, ìyá Sólómónì wá. Bátíṣébà sì bi í pé, “Àlàáfíà ni o bá wa bí?”Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni.”

14. Nígbà náà ni ó sì fi kún un pé, “Mo ní ohun kan láti sọ fún ọ.”Bátíṣébà sì wí pé, “Má a wí.”

15. Ó wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí o ti mọ̀, ti tèmi ni ìjọba náà. Gbogbo Ísírẹ́lì ti wò mí bí ọba wọn. Ṣùgbọ́n nǹkan yípadà, ìjọba náà sì ti lọ sí ọ̀dọ̀ arákùnrin mi, nítorí ó ti wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa wá.

16. Nísinsìnyí mo ní ìbéèrè kan láti bi ọ́, má ṣe kọ̀ fún mí.”Ó wí pé, “O lè wí.”

17. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ̀ṣíwájú pé, “Mo bẹ̀ ọ́, jọ̀wọ́ sọ fún Sólómónì ọba (Òun kì yóò kọ̀ fún ọ́) kí ó fún mi ní Ábíságì ará Súnémù ní aya.”

18. Bátíṣébà sì dáhùn pé, “Ó dára èmi yóò bá ọba sọ̀rọ̀ nítorí rẹ̀.”

Ka pipe ipin 1 Ọba 2