Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 2:29-39 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. A sì sọ fún Sólómónì ọba pé Jóábù ti sá lọ sínú àgọ́ Olúwa àti pé ó wà ní ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ. Nígbà náà ni Sólómónì pàṣẹ fún Bénáyà ọmọ Johóíadà pé, “Lọ, kí o sì kọlù ú.”

30. Bénáyà sì wọ inú àgọ́ Olúwa, ó sì wí fún Jóábù pé, “Ọba sọ wí pé, Jáde wá.”Ṣùgbọ́n ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Èmi yóò kú níhìn ín.”Bénáyà sì mú èsì fún ọba, “Báyìí ni Jóábù ṣe dá mi lóhùn.”

31. Ọba sì pàṣẹ fún Bénáyà pé, “Ṣe bí ó ti wí. Kọ lù ú, kí o sì sin ín, kí o sì mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi àti kúrò lọ́dọ̀ ilé bàbá mi, tí Jóábù ti ta sílẹ̀.

32. Olúwa yóò sì san ẹ̀jẹ̀ tí ó ti ta sílẹ̀ padà fún un, nítorí tí ó kọlu ọkùnrin méjì, ó sì fi idà rẹ̀ pa wọ́n, Dáfídì bàbá mi kò sì mọ̀ àwọn méjèèjì ni. Ábínérì ọmọ Nérì olórí ogun Ísírẹ́lì, àti Ámásà ọmọ Jétérì olórí ogun Júdà, wọ́n jẹ́ olódodo, wọ́n sì sàn ju òun fúnrarẹ̀ lọ.

33. Kí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn wá sórí Jóábù àti sórí irú-ọmọ rẹ̀ títí láé. Ṣùgbọ́n sórí Dáfídì àti irú-ọmọ rẹ̀, sí ilé rẹ̀ àti sí ìtẹ́ rẹ̀, ni kí àlàáfíà Olúwa wà títí láé.”

34. Bẹ́ẹ̀ ni Bénáyà ọmọ Jéhóíádà sì gòkè lọ, ó sì kọlu Jóábù, ó sì pa á, a sì sin ín ní ilẹ̀ ibojì ara rẹ̀ ní ihà.

35. Ọba sì fi Bénáyà ọmọ Jéhóíádà jẹ olórí ogun ní ipò Jóábù àti Sádókù àlùfáà ní ipò Ábíátarì.

36. Nígbà náà ni ọba ránṣẹ́ sí Ṣíméhì ó sì wí fún un pé, “Kọ́ ilé fún ara rẹ ní Jérúsálẹ́mù, kí o sì máa gbé ibẹ̀, ṣùgbọ́n kí o má sì ṣe lọ sí ibòmíràn.

37. Ọjọ́ tí ìwọ bá jáde, tí o sì kọjá pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kídírónì, kí ìwọ kí ó mọ̀ dájúdájú pé ìwọ yóò kú; ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wà lórí ara rẹ.”

38. Ṣíméhì sì dá ọba lóhùn pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára. Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe bí Olúwa mi ọba ti wí.” Ṣíméhì sì gbé ní Jérúsálẹ́mù fún ìgbà pípẹ́.

39. Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ Síméì méjì sì sá lọ sọ́dọ̀ Ákíṣì ọmọ Máákà, ọba Gátì, a sì sọ fún Síméì pé, “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ méjì wà ní Gátì.”

Ka pipe ipin 1 Ọba 2