Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 19:12-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Lẹ́yìn ìsẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.

13. Nígbà tí Èlíjà sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà.Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Èlíjà?”

14. Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti kọ májẹ̀mu rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”

15. Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí ihà Dámásíkù. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hásáélì ní ọba lórí Árámù.

16. Tún fi òróró yan Jéhù ọmọ Nímísì ní ọba lórí Ísírẹ́lì, àti kí o fi òróró yan Èlíṣà ọmọ Sáfátì, ará Ábélí-Méhólà ní wòlíì ní ipò rẹ.

17. Jéhù yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hásáélì, Èlíṣà yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jéhù.

18. Ṣíbẹ̀, Èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàarin (700) ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Ísírẹ́lì, àní gbogbo eékún tí kò ì tíì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Báálì, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”

19. Bẹ́ẹ̀ ni Èlíjà lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Èlíṣà ọmọ Sáfátì. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú ìkéjìlá. Èlíjà sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.

Ka pipe ipin 1 Ọba 19