Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 11:4-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Bí Sólómónì sì ti di arúgbó, àwọn ìyàwó rẹ̀ sì yí i ní ọkàn padà sí ọlọ́run mìíràn, ọkàn rẹ̀ kò sì ṣe déédé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dáfídì bàbá rẹ̀ ti ṣe.

5. Ó tọ Ásítórétì òrìṣà àwọn ará Sídónì lẹ́yìn, àti Mílíkómì òrìṣà ìríra àwọn ọmọ Ámónì.

6. Bẹ́ẹ̀ ni Sólómónì ṣe búburú níwájú Olúwa; kò sì tọ Olúwa lẹ́yìn ní pípé, bí Dáfídì bàbá rẹ̀ ti ṣe.

7. Lórí òkè tí ń bẹ níwájú Jérúsálẹ́mù, Sólómónì kọ́ ibi gíga kan fún Kémósì, òrìṣà ìríra Móábù, àti fún Mólékì, òrìṣà ìríra àwọn ọmọ Ámónì.

8. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe bẹ́ẹ̀ fún gbogbo àwọn àjèjì obìnrin rẹ̀, ẹni tí ń sun tùràrí, tí wọ́n sì ń rúbọ fún òrìṣà wọn.

9. Olúwa bínú sí Sólómónì nítorí ọkàn rẹ̀ ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì, tí ó ti fi ara hàn án lẹ́ẹ̀méjì.

10. Bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti kìlọ̀ fún Sólómónì kí ó má ṣe tọ àwọn Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn, ṣùgbọ́n Sólómónì kò pa àṣẹ Olúwa mọ́.

Ka pipe ipin 1 Ọba 11