Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 10:25-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Bí ọdún ṣe ń gorí ọdún olúkúlùkù àwọn tí ń wá sì ń mú ẹ̀bùn tirẹ̀ wá, ohun èlò fàdákà àti ohun èlò wúrà àti ẹ̀wù, àti tùràrí olóòórùn dídùn, ẹṣin àti ìbááka.

26. Sólómónì sì kó kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jọ; ó sì ní egbèje (1400) kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàata (13,000) ẹlẹ́ṣin, tí ó fi pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ àti pẹ̀lú rẹ̀ ní Jérúsálẹ́mù.

27. Ọba sì jẹ́ kí fàdákà pọ̀ ní Jérúsálẹ́mù bí òkúta, àti igi kédárì ni ó ṣe kí ó dàbí igi síkámórè tí ń bẹ ní àfonífojì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀.

28. A sì mú ẹṣin wá fún Sólómónì láti Éjíbítì ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́, oníṣòwò ọba ni ó ń mú wọn wá fún òwe.

29. Wọ́n ń mú kẹ̀kẹ́ kan gòkè láti Éjíbítì wá fún ẹgbẹ̀ta (600) ṣékélì fàdákà àti ẹsin kan fún àádọ́jọ (150). Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún mú wọn wá fún ọba àwọn ọmọ Hítì àti ọba àwọn ọmọ Árámánì.

Ka pipe ipin 1 Ọba 10