Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 1:33-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Ó sì wí fún wọn pé: “Ẹ mú àwọn ìránṣẹ́ Olúwa yín pẹ̀lú yín kí ẹ sì mú kí Sólómónì ọmọ mi kí ó gun ìbaka mi, kí ẹ sì mú-un sọ̀kalẹ̀ wá sí Gíhónì.

34. Níbẹ̀ ni Sádókù àlùfáà àti Nátanì wòlíì fi òróró yàn án ní ọba lórí Ísírẹ́lì. Ẹ fọn fèrè, kí ẹ sì ké pé, ‘Kí Sólómónì ọba kí ó pẹ́!’

35. Nígbà náà ni kí ẹ sì gòkè pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì wá, kí ó sì jókòó sórí ìtẹ́ mi, kí ó sì jọba ní ipò mi. Èmi ti yàn án ní ọba lórí gbogbo Ísírẹ́lì àti Júdà.”

36. Bénáyà ọmọ Jéhóíádà sì dá ọba lóhùn pé, “Àmín! Kí Olúwa Ọlọ́run Olúwa mi ọba, kéde rẹ̀ bẹ́ẹ̀

Ka pipe ipin 1 Ọba 1