Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 8:29-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Jélíélì, baba a Gíbíónì ń gbé ní Gíbíónì.Ìyáwó o Rẹ̀ a má jẹ́ Mákà,

30. Àkọ́bí Rẹ̀ a sì má a jẹ́ Ábídónì wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Ṣúrì, Kíṣì, Báláhì, Nérì, Nádábù,

31. Gédórì Áhíò, Ṣékérì

32. Pẹ̀lú Míkílótì, tí ó jẹ́ bàbá Ṣíméà. Wọ́n ń gbé lébá ìbátan wọn ní Jérúsálẹ́mù.

33. Mérì jẹ́ baba Kíṣì, Kíṣì baba Ṣọ́ọ̀lù àti Ṣọ́ọ̀lù baba Jónátanì, Málìkíṣúà, Ábínádábù àti Ésíbálì.

34. Ọmọ Jónátanì:Méríbáì tí ó jẹ́ baba Míkà.

35. Àwọn ọmọ Míkà:Pítónì, Mélékì, Táréà, àti Áhásì.

36. Áhásì jẹ́ bàbá a Jéhóádá, Jéhóádá jẹ́ baba a Álémétì Áṣíméfétì àti Ṣímírì, Ṣímírì sì jẹ́ baba a Móṣà.

37. Móṣà jẹ́ baba a Bínéà; Ráfà sì jẹ́ ọmọ Rẹ̀, Éléásà ọmọ Rẹ̀ àti Áṣélì ọmọ Rẹ̀.

38. Áṣélì ní ọmọ mẹ́fà pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn:Áṣíríkámù, Bókérù, Íṣímáélì, Ṣéáríà, Ọbádáyà àti Hánánì. Gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Áṣélì.

39. Àwọn ọmọ arákùnrin Rẹ̀ Éṣékì:Úlámù àkọ́bí Rẹ̀, Jéúṣì ọmọkùnrin ẹ̀ẹ̀kejì àti Élífélétì ẹ̀ẹ̀kẹ́ta.

40. Àwọn ọmọ Úlámù jẹ́ ògboyà jagunjagun tí ó lè gbá orin mú. Wọ́n ní ọ̀pọ̀ ọmọkùnrin àti ọmọ ọmọkùnrin márùndínlọ́gọ́jọ ní gbogbo Rẹ̀.Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ìran ọmọ Bẹ́ńjámínì.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 8