Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 5:24-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Éférì, Ísì, Élíélì, Ásíríélì, Jérémáíà, Hódáfíà àti Jáhídíélì àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn.

25. Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì se àgbérè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn.

26. Nítorí náà Ọlọ́run Ísírẹ́lì ru ẹmi Púlù ọba Ásíríà sókè, ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Rúbẹ́nì àti àwọn ọmọ Gádì, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè, ó sì kó wọn wá sí Hálà, àti Hábórì, àti Hárà, àti sí ọ̀dọ̀ Gósánì; títí dí òní yìí.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 5